74:1
Ìwọ olùdaṣọbora.
74:2
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
74:3
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
74:4
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
74:5
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
74:6
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
74:7
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
74:8
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
74:9
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
74:10
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
74:11
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan (ìyẹn nínú ikùn ìyá rẹ̀).
74:12
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
74:13
àti àwọn ọmọkúnrin tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
74:14
Mo sì fi àyè ìrọ̀rùn gbá a dáadáa.
74:15
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
74:16
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
74:17
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná)[1].
74:18
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
74:19
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
74:20
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
74:21
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
74:22
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
74:23
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìndà, ó sì ṣègbéraga.
74:24
Ó sì wí pé: “Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
74:25
Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara”
74:26
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
74:27
Kí l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ iná Saƙọr?
74:28
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.[1]
74:29
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
74:30
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
74:31
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: “Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?” Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
74:32
Ẹ gbọ́! Allāhu fi òṣùpá búra.
74:33
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.
74:34
Ó tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́ búra.
74:35
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) tó tóbi.
74:36
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
74:37
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn (nínú ẹ̀ṣẹ̀).
74:38
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun tó ṣe níṣẹ́.
74:39
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
74:40
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
74:41
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
74:42
“Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?”
74:43
Wọn yóò wí pé: “Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
74:44
Àwa kò sì sí nínú àwọn tó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
74:45
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
74:46
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́
74:47
títí ikú fi dé bá wa.”
74:48
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
74:49
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
74:50
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń sá lọ,
74:51
tó sá fún kìnìhún?
74:52
Rárá, ńṣe ni ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
74:53
Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.
74:54
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
74:55
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́, kí ó rántí rẹ̀.
74:56
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì ni àforíjìn.